“Gbọ̀ngàn John Randle, jẹ àkọ́kọ́ lára ọ̀pọ̀lọpọ̀ àfojúsùn tí a ti là kalẹ̀ láti ṣe ìpamọ́ ogún-ìbí Yorùbá, láti ara àyẹ́sí àti ìpamọ́ ìtàn àti àṣà, àtúgbédìde àwọn ibi àtijọ́ tí wọ́n ti di àlòpatì, àwọn ibi ìgbáfẹ́ ará ìlú àti àtúngbédìdì iyì ìlú. Oníkán máa dí ibi ìyànjú fún àdúgbò tí ó jojúnígbèsè tí ó sì fi àyè gba ìrìnkiri afẹ́ ní àárín gbùngbùn ìlú Èkó.”

Babajide Sanwoolu, Gómínà Ìpínlẹ̀ Èkó

All images © Ademola Olaniran & Jide Atobatele

Gbọ̀ngàn John Randle fún Àṣà àti Ìtàn Yorùbá

Gbọ̀ngàn John Randle jẹ́ oun àgbékalẹ̀ ńlá nínú ìṣàfihàn oun mèremère ọnà (mùsíọ́mù) l’Áfrikà. Ó jẹ́ ìgbélárugẹ ńlá fún àṣà àti ìṣe Yorùbá  – láti àtẹ̀yìnwá, dé lọwọ́lọ́wọ́, àti sí ọjọ́ iwájú.  

Nínú àárín gbùngbùn ìmúwásípò Ìṣàlẹ̀ Èkó, ó jẹ́ ibùdó pàtàkì tí a ṣe fún àwọn arìnrìàjò ilẹ̀ yìí àti ìlú òkèèrè.

Iṣẹ́ àkànṣẹ yìí tí ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó fi tàṣẹtàṣẹ sọlẹ̀, wà ní ibití ó rọrùn púpọ̀ láti dé ní àárin gbùngbùn àdúgbò Màrínà àti Oníkán. 

Fún bíi àádọ́rùn-ún ọdún, Gbọ̀ngàn John Randle ní Oníkán ní Èkó dúró gẹ́gẹ́ bí ibi ìgbafẹ́ tí àwọn ènìyàn ti máa ń lúwẹ̀ẹ́, ṣafẹ́, tí wọ́n sì máa ń dá ara wọn lárayá. Ibi ìúwẹ̀ẹ́  tí ó wà ní ibẹ̀ ni èyí ti Dókítà. John Randle fi lọ́lẹ̀ pẹ̀lú èròńgbà láti máa lò ó, láti kọ́ àwọn ará Èkó tí wọ́n bá fẹ́ kọ́ bí a ṣe ń lúwẹ̀ẹ́. Ibi ilúwẹ̀ẹ́ kò ní yọ kúro nínú àtúnṣẹ tuntun sí ibi-iṣẹ́ náà. 

Gbọ̀ngàn yìí máa ní àwọn ohun ìní lọ́pọ̀lọpọ̀, lára èyí tí ibi ìsàfihàn tí ó gbayì yóò wà. 

Àlàyé kíkún nípa ọjọ́ ìṣíde, wákàtí tí yóò jẹ́, àti owó ìwọlé  fún ìṣíde ọdún 2021 yóò máà tẹ̀ta láìpẹ́. Kọ́ Síi...